2 Ọba 16:13-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Ó sì ṣun ẹbọ ọrẹ-ṣíṣun rẹ̀ àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, o si ta ohun-mímu rẹ̀ sílẹ̀, ó sì wọ́n èjẹ̀ ọrẹ-àlàáfíà rẹ̀ sí ará pẹpẹ náà.

14. Ṣùgbọ́n ó mú pẹpẹ idẹ tí ó wà níwájú Olúwa kúrò láti iwájú ilé náà, láti àárin méjì pẹpẹ náà, àti ilé Olúwa, ó sì fi í sí apá àríwá pẹpẹ náà.

15. Áhásì ọba sì pàṣẹ fún Úráyà àlùfáà, wí pé, “Lórí pẹpẹ ńlá náà ni kó o máa ṣun ọrẹ-ṣíṣun òròwúrọ̀ àti ọrẹ-jijẹ alaalẹ́, àti ẹbọ ṣíṣun ti ọba, àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, pẹ̀lú ọrẹ ṣíṣun tí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọrẹ jíjẹ wọn, àti ọrẹ ohun mímu wọn; kí o sì wọ́n gbogbo ẹ̀jẹ̀ ọrẹ-sísun náà lórí rẹ̀, àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ mìíràn: ṣùgbọ́n ní ti pẹpẹ idẹ náà èmi ó máa gbèrò ohun tí èmi ó fi ṣe.”

16. Báyìí ni Úráyà àlùfáà ṣe, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Áhásì ọba pa láṣẹ.

2 Ọba 16