2 Ọba 13:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọdún kẹtàlélógún ti Jóásì ọmọ ọba Áhásáyà ti Júdà, Jéhóáhásì ọmọ Jéhù di ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà. Ó sì jọba fún ọdún mẹ́tadínlógún.

2. Ó ṣe búburú níwájú Olúwa nípa títẹ̀lé ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì, èyí tí ó ti fa Ísírẹ́lì láti dá, kò sì yípadà kúrò nínú wọn.

3. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, àti fún ìgbà pípẹ́, ó fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ agbára ọba Hásáélì ọba Ṣíríà àti Bẹni-Hádádì ọmọ rẹ̀.

4. Nígbà náà Jéhóáhásì kígbe ó wá ojú rere Olúwa, Olúwa sì tẹ́tí sí i. Nítorí ó rí bí ọba Ṣíríà ti ń ni Ísírẹ́lì lára gidigidi.

5. Olúwa pèsè Olùgbàlà fún Ísírẹ́lì, wọ́n sì sá kúrò lọ́wọ́ agbára Ṣíríà. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbé nínú ilé ara wọn gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà tẹ́lẹ̀.

2 Ọba 13