2 Kọ́ríńtì 4:9-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. A ń ṣe inúnibíni sí wa, ṣùgbọ́n a kò kọ̀ wá sílẹ̀; a ń rẹ̀ wá sílẹ̀ ṣùgbọ́n a kò pa wá run.

10. Nígbà gbogbo àwa ń ru ikú Jésù Olúwa kiri ni ará wa, kí a lè fi ìyè Jésù hàn pẹ̀lú lará wa.

11. Nítorí pé nígbà gbogbo ní a ń fí àwa tí ó wà láàyè fún ikú nítorí Jésù, kí a lè fi ìyè hàn nínú ara kíkú wa pẹ̀lú.

12. Bẹ́ẹ̀ ni ikú ń ṣiṣẹ́ nínú wa, ṣùgbọ́n ìyè ṣiṣẹ́ nínú yín.

13. Bí a ti kọ́, “Èmi ìgbàgbọ́, nítorí náà ni Èmi ṣe sọ.” pẹ̀lú ẹ̀mí ìgbàgbọ́ kan náà a tún gbàgbọ́ àti nítorí náà ni àwa sì ṣe ń sọ.

2 Kọ́ríńtì 4