2 Kọ́ríńtì 1:20-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

20. Nítorí tí gbogbo ìlérí Ọlọ́run dí bẹ́ẹ̀ ni nínú Kírísítì. Nítorí ìdí èyí ní a ṣe ń wí pé “Àmín” nípaṣẹ̀ rẹ̀ sí ògo Ọlọ́run.

21. Ǹjẹ́ níṣinṣin yìí, Ọlọ́run ni ó fí ẹsẹ̀ wa múlẹ̀ pẹ̀lú yín nínú Kírísítì, Òun ni ó ti fi àmì òróró yàn wá,

22. ó sì fí èdìdì rẹ̀ dì wá pẹ̀lú, ó sì tí fi Ẹ̀mí rẹ́ sí wa ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí ìdánilójú ohun tí ó ń bọ̀.

23. Mo sì pe Ọlọ́run ṣe ẹlẹ́rìí ọkàn mi pé nítorí àtidá yín sí ní èmi kò ṣe padà sí Kọ́ríńtì.

24. Kì í ṣe nítorí tí àwa jẹ gàba lórí ìgbàgbọ́ yín: ṣùgbọ́n àwa ń ṣisẹ́ pọ̀ pẹ̀lú yín fún ayọ̀ yín nítorí nípa ìgbàgbọ́ ni ẹ̀yin dúró sinisin.

2 Kọ́ríńtì 1