2 Kíróníkà 22:7-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ní gbogbo ìgbà ìbẹ̀wò Áhásáyà sí Jórámí, Ọlọ́run mú ìṣubú Áhásáyà wá. Nígbà tí Áhásáyà dé, ó jáde lọ pẹ̀lú Jórámì láti lọ bá Jéhù ọmọ Nímísì, ẹni tí Olúwa ti fi àmì òróró yàn láti pa ìdílé Áhábù run.

8. Nígbà tí Jéhù ń ṣe ìdájọ́ lórí ilé Áhábù. Ó rí ọmọbìrin ọba ti Júdà àti àwọn ọmọkùnrin ìbátan Áhásì. Tí ó ń dásí Áhásáyà, ó sì pa wọ́n.

9. Ó lọ làti wá Áhásáyà, àti àwọn ọkùnrin rẹ̀. Àwọn arákùnrin rẹ̀ ṣẹ́gun rẹ̀ nígbà tí ó sá pamọ́ ní Saaríà. A gbé e wá sí ọ̀dọ̀ Jéhù, a sì pa á. Wọ́n sin ín nítorí wọ́n wí pé “Ọmọkùnrin Jèhóṣáfátì ni, ẹni tí ó wá Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan ní ilé Áhásáyà tí ó lágbára láti gbé ìjọba náà dúró.

2 Kíróníkà 22