1 Tímótíù 4:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. NÍṢÍNṢIN YÌÍ, èmi ń tẹnumọ́ ọ́ pé ní ìgbà ìkẹyìn àwọn mìíràn yóò kúrò nínú ìgbàgbọ́, wọn yóò máa fiyèsí àwọn ẹ̀mí tí ń tannijẹ, àti ẹ̀kọ́ àwọn ẹ̀mí èsù.

2. Nípa àgàbàgebè àwọn tí ń ṣèké, àwọn tí ọkàn tìkarawọn dàbí èyí tí a fi irin gbígbóná jó.

3. Àwọn tí ń dá-ni-lẹ́kun láti gbéyàwó ti wọn si ń pàṣẹ láti ka èèwọ̀ oúnjẹ ti Ọlọ́run ti dá fún ìtẹ́wọ́gbà pẹ̀lú ọpẹ́ àwọn onígbàgbọ́ àti àwọn ti ó mọ òtítọ́.

4. Nítorí gbogbo ohun ti Ọlọ́run dá ni ó dára, kò sí ọkàn tí ó yẹ kí a kọ̀, bí a bá fi ọpẹ́ gbà á.

5. Nítorí tí a fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run àti àdúrà yà á sí mímọ́.

6. Bí ìwọ bá ń rán àwọn ará létí nǹkan wọ̀nyí, ìwọ ó jẹ́ iránṣẹ́ rere ti Kírísítì Jésù, tí a fi ọ̀rọ̀ ìgbàgbọ́ àti ẹ̀kọ́ rere bọ́, èyí ti ìwọ ti ń tẹ̀lé.

1 Tímótíù 4