1 Tímótíù 3:13-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Nítorí àwọn tí ó lo ipò díákónì dáradára ra ipò rere fún ara wọn, àti ìgboyà púpọ̀ nínú ìgbàgbọ́ tí ń bẹ nínú Kírísítì Jésù.

14. Ìwé nǹkan wọ̀nyí ni mo kọ sí ọ, mo sì ń réti àti tọ̀ ọ́ wá ní lọ́ọ́lọ́ọ́.

15. Ṣùgbọ́n bí mo bá pẹ́, kí ìwọ lè mọ̀ bí ó ti yẹ fún àwọn ènìyàn láti máa hùwà nínú ilé Ọlọ́run, tì í ṣe ìjọ Ọlọ́run, alààyè, ọ̀wọ́n àti ìpìlẹ̀ òtítọ́.

16. Láìṣiyè méjì, títóbi ní ohun ìjìnlẹ̀ ìwà-bí-Ọlọ́run:ẹni tí a fi hàn nínú ara,tí a dáláre nínú Ẹ̀mí,ti àwọn ańgẹ́lì rí,tí a wàásù rẹ̀ láàrin àwọn orílẹ̀-èdè,tí a gbàgbọ́ nínú ayé,tí a sì gbà sókè sínú ògo.

1 Tímótíù 3