1 Tímótíù 1:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Ṣùgbọ́n nítorí èyí ni mo ṣe rí àánú gbà, pé lára mi, bí olórí ẹlẹ́sẹ̀ ni kí Jésù Kírísítì fi gbogbo ìpamọ́ra rẹ̀ hàn bí àpẹẹrẹ fún àwọn tí yóò gbà á gbọ́ sí ìyè àìnípẹ̀kun ìkẹyìn.

17. Ǹjẹ́ fún Ọba ayérayé, àìdíbàjẹ́, àìrí, Ọlọ́run kan ṣoṣo, ni ọlá àti ògo wà fún láéláé. Àmín.

18. Àṣẹ yìí ni mo pa fún ọ, Tímótíù ọmọ mi, gẹ́gẹ́ bí ìsọtẹ́lẹ̀ wọ̀nyí tó ó ti ṣáájú nípa rẹ̀, pé nípaṣẹ̀ wọ́n kí ìwọ lè máa ja ìjà rere;

19. Máa ní ìgbàgbọ́ àti ẹ̀rí-ọkàn rere. Àwọn ẹlòmíràn tanù lọ́dọ̀ wọn tí wọ́n sì rí ọkàn ìgbàgbọ́ wọn;

20. Nínú àwọn ẹni tí Híménéù àti Alẹkisáńdérù wà; àwọn tí mo ti fi lé Sàtánì lọ́wọ́, kí a lè kọ́ wọn kí wọn má sọ̀rọ̀-òdì mọ́.

1 Tímótíù 1