1. Nígbà náà ni àwọn ará Sífì tọ Ṣọ́ọ̀lù wá sí Gíbéà, wọn wí pé, “Dáfídì kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hákílà, èyí tí ó wà níwájú Jésímónì?”
2. Ṣọ́ọ̀lù sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sífì ẹgbẹ̀ẹ́dógún àṣàyàn ènìyàn ni Ísírẹ́lì sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dáfídì ni ijù Sífì.
3. Ṣọ́ọ̀lù sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hákílà tí o wà níwájú Jésímónì lójú ọ̀nà, Dáfídì sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Ṣọ́ọ̀lù ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.