1 Sámúẹ́lì 26:1-3 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nígbà náà ni àwọn ará Sífì tọ Ṣọ́ọ̀lù wá sí Gíbéà, wọn wí pé, “Dáfídì kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hákílà, èyí tí ó wà níwájú Jésímónì?”

2. Ṣọ́ọ̀lù sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sífì ẹgbẹ̀ẹ́dógún àṣàyàn ènìyàn ni Ísírẹ́lì sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dáfídì ni ijù Sífì.

3. Ṣọ́ọ̀lù sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hákílà tí o wà níwájú Jésímónì lójú ọ̀nà, Dáfídì sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Ṣọ́ọ̀lù ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.

1 Sámúẹ́lì 26