11. Sólómónì ọba sì fi ogún ìlú ní Gálílì fún Hírámù ọba Tírè, nítorí tí Hírámù ti bá a wá igi kédárì àti igi fírì àti wúrà gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìfẹ́ rẹ̀.
12. Ṣùgbọ́n nígbà tí Hírámù sì jáde láti Tírè lọ wo ìlú tí Sólómónì fi fún un, inú rẹ̀ kò sì dùn sí wọn.
13. Ó sì wí pé, “Irú ìlú wo nì wọ̀nyí tí ìwọ fi fún mi, arákùnrin mi?” Ó sì pè wọ́n ní ilẹ̀ kábúlù títí fi di òní yìí.
14. Hírámù sì ti fi ọgọ́fà (120) talẹ́ntì wúrà ránṣẹ́ sí ọba.
15. Ìdí àwọn asìnrú ti Sólómónì ọba kójọ ni èyí; láti kọ́ ilé Olúwa àti ààfin òun tìkárarẹ̀; Mílò, odi Jérúsálẹ́mù, Hásórì, Mégídò àti Gésérì.
16. Fáráò ọba Éjíbítì sì ti kọlu Gésérì, ó sì ti fi iná sun ún, ó sì pa àwọn ará Kénánì tí ń gbé ìlú náà, ó sì fi ta ọmọbìnrin rẹ̀, aya Sólómónì lọ́rẹ.