1 Ọba 4:7-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Sólómónì sì tún ní ìjòyè méjìlá lórí gbogbo agbégbé Ísírẹ́lì, tí wọ́n ń pèsè oúnjẹ fún ọba àti agbo ilé rẹ̀. Olúkúlùkù ní láti pèsè fún oṣù kan ní ọdún.

8. Orúkọ wọn ni wọ̀nyí:Bénhúrì ní ìlú olókè Éfúráímù.

9. Beni-Dékérì ní Mákásì, Ṣáíbímù, Bẹti-Sémésì, àti Eloni-Bétíhánánì;

10. Beni-Hésédì, ní Árúbótì; tirẹ̀ ni Sókò àti gbogbo ilẹ̀ Héférì ń ṣe;

11. Beni-Ábínádábù, ní Napoti Dórì; òun ni ó fẹ́ Táfátì ọmọbìnrin Sólómónì ní aya.

12. Báánà ọmọ Áhílúdì, ní Táánákì àti Mégídò, àti ní gbogbo Bétísánì tí ń bẹ níhà Saritanà níṣàlẹ̀ Jésérẹ́lì, láti Bétísánì dé Abeli-Méhólà títí dé ibi tí ń bẹ ní ìkọjá Jókínéámù;

13. Bẹni-Gébérì ní Rámótì-Gílíádì; tirẹ̀ ni àwọn ìletò Jáírì ọmọ Mànásè tí ń bẹ ní Gílíádì, tirẹ̀ sì ni agbégbé Ágóbù, tí ń bẹ ní Básánì, ọgọ́ta (60) ìlú tí ó tóbi pẹ̀lú odi tí ẹnu ọ̀nà rẹ̀ jẹ́ irin.

14. Áhínádábù ọmọ Ídò ní Máhánáímù

15. Áhímásì ní Náfítalì; ó fẹ́ Básémátì ọmọbìnrin Sólómónì ní aya;

16. Báánà ọmọ Húṣáì ní Ásérì àti ní Álótì;

17. Jèhósáfátì ọmọ Párúhà ni ó wà ní Ísákárì;

18. Síméì ọmọ Élà ni Bẹ́ńjámínì;

19. Gébérì ọmọ Úrì ní Gílíádì; orílẹ̀ èdè Ṣíhónì ọba àwọn ará Ámórì àti orílẹ̀ èdè Ógù ọba Básánì. Òun nìkan ni ìjòyè lórí ilẹ̀ náà.

1 Ọba 4