1 Ọba 12:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. ‘Báyìí ni Olúwa wí: Ẹ má ṣe gòkè lọ láti bá àwọn arákùnrin yín jà, àwọn ènìyàn Ísírẹ́lì. Ẹ padà, olúkúlùkù yín sí ilé rẹ̀, nítorí nǹkan yìí láti ọ̀dọ̀ mi wá ni.’ ” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, wọ́n sì tún padà sí ilé wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.

25. Nígbà náà ni Jéróbóámù kọ́ Ṣékémù ní òkè Éfúráímù, ó sì ń gbé inú rẹ̀. Láti ibẹ̀ ó sì jáde lọ, ó sì kọ́ Pénúélì.

26. Jéróbóámù rò nínú ara rẹ̀ pé, “Ìjọba náà yóò padà nísinsìnyìí sí ilé Dáfídì.

27. Bí àwọn ènìyàn wọ̀nyí bá gòkè lọ láti ṣe ìrúbọ ní ilé Olúwa ní Jérúsálẹ́mù, wọn yóò tún fi ọkàn wọn fún Olúwa wọn, Réhóbóámù ọba Júdà. Wọn yóò sì pa mí, wọn yóò sì tún padà tọ Réhóbóámù ọba Júdà lọ.”

28. Lẹ́yìn tí ó ti gba ìmọ̀ràn, ọba sì yá ẹgbọ̀rọ̀ màlúù wúrà méjì. Ó sì wí fún àwọn ènìyàn pé, “Ó ti pọ̀jù fún yín láti máa gòkè lọ sí Jérúsálẹ́mù. Àwọn Ọlọ́run yín nìyìí, Ísírẹ́lì, tí ó mú yín láti ilẹ̀ Éjíbítì wá.”

1 Ọba 12