1 Kọ́ríńtì 12:25-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

25. Kí ó má ṣe sí ìyàtọ̀ nínú ara, ṣùgbọ́n kí àwọn ẹ̀yà ara le máa jẹ́ olùrànlọ́wọ́ fún ara wọn.

26. Bí ẹ̀yà ara kan bá ń jìyà, gbogbo àwọn ẹ̀yà ara ìyókù a máa bá a pín nínú ìyà náà. Tí a bá sì bu ọlá fún ẹ̀yà ara kan, gbogbo ẹ̀yà ara ìyókù a máa bá a yọ̀.

27. Gbogbo yín jẹ́ ara Kírísítì, ẹnìkọ̀ọ̀kan yín sì jẹ́ ẹ̀yà ara ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ nínú ara Kírísítì.

28. Àti nínú ìjọ, Olọ́run ti yan àwọn àpósítélì àkọ́kọ́, èkéjì àwọn wòlíì, ẹni ẹ̀kẹta àwọn Olùkọ́, lẹ́yìn náà, àwọn tí ó ní òsìsẹ́ iṣẹ́ ìyanu, lẹ́yin náà àwọn tí ó ní ẹ̀bùn ìmuláradá, àwọn Olùrànlọ́wọ́ àwọn alákòóso àwọn tí ń sọ onírúurú èdè.

1 Kọ́ríńtì 12