1 Kọ́ríńtì 1:28-31 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

28. Ó ti yan ètò tí ayé kẹ́gàn, tí wọn kò kà sí rárá, láti sọ nǹkan tí wọ́n kà sí ńlá di ohun asán àti aláìwúlò.

29. Nítorí kí ó má ba à sí ẹnìkan tí yóò ṣògo níwájú rẹ̀.

30. Nítorí rẹ̀ ni ẹ̀yin ṣe wà nínú Kírísítì Jésù ẹni ti ó já sí ọgbọ́n fún wa láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run—èyi ń ni, òdodo, ìwà mímọ́ àti ìràpadà wa.

31. Nítorí náà, bí a ti kọ ọ́ pé, “Ẹni ti ó bá ń ṣògo kí ó máa ṣògo nínú Olúwa.”

1 Kọ́ríńtì 1