1 Kíróníkà 9:34-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

34. Gbogbo wọ̀nyí jẹ́ olórí àwọn Léfì, olóyè gẹ́gẹ́ bí a ti se kọ lẹ́sẹsẹ sínú ìtàn ìdílé láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn, wọ́n sì ń gbé ní Jérúsálẹ́mù.

35. Jélíélì baba Gíbíónì ń gbé ní Gíbíónì.Orúkọ ìyàwó Rẹ̀ a má a jẹ́ Mákà,

36. Pẹ̀lú àkọ́bí ọmọkùnrin Rẹ̀ jẹ́ Ábídónì, tí wọ̀nyí sì ń tẹ̀lé Ṣúrì, Kíṣì Bálì, Nérì, Nádábù.

37. Gédórì, Áhíò, Sékaráyà àti Míkílótì.

38. Míkílótì jẹ́ baba Ṣíméámì, àwọn náà ń gbé ní ẹ̀bá ìbátan wọn ní Jérúsálẹ́mù.

39. Nérì jẹ́ baba Kíṣì, Kíṣì baba a Ṣọ́ọ̀lù, àti Ṣọ́ọ̀lù baba a Jónátanì, àti Málíkíṣuà, Ábínádábù àti Éṣí-Bálì.

40. Ọmọ Jónátanì:Méríbú Bálì, tí ó jẹ́ baba a Míkà:

41. Àwọn ọmọ Míkà:Pítónì. Mélékì, Táhíréà àti Áhásì.

42. Áhásì jẹ́ baba Jádà, Jádà jẹ́ baba Álémétì, Aṣimáfétì, Ṣímírì, sì Ṣímírì jẹ́ baba Móṣà.

43. Móṣà jẹ́ baba Bínéà; Réfáíà jẹ́ ọmọ Rẹ̀, Éléásà ọmọ Rẹ̀ àti Áṣélì ọmọ Rẹ̀.

1 Kíróníkà 9