Owe 22:10-15 Yorùbá Bibeli (YCE)

10. Ṣá ẹlẹgàn tì sode, ìja yio si jade; nitõtọ ìja ati ẹ̀gan yio dẹkun.

11. Ẹniti o fẹ ìwa funfun aiya, ti o fẹ ọ̀rọ pẹlẹ, ọba yio ṣe ọrẹ́ rẹ̀.

12. Oju Oluwa pa ìmọ mọ́, o si yi ọ̀rọ olurekọja po.

13. Ọlẹ wipe, kiniun mbẹ lode, a o pa mi ni igboro.

14. Ẹnu awọn ajeji obinrin, iho jijin ni; ẹniti a mbinu si lati ọdọ Oluwa wá ni yio ṣubu sinu rẹ̀.

15. Li aiya ọmọde ni wère dì si; ṣugbọn paṣan itọ́ni ni yio le e jina kuro lọdọ rẹ̀.

Owe 22