O. Daf 38:18-22 Yorùbá Bibeli (YCE)

18. Nitori ti emi o jẹwọ ẹ̀ṣẹ mi; emi o kãnu nitori ẹ̀ṣẹ mi.

19. Ṣugbọn ara yá awọn ọta mi, ara wọn le; awọn ti o korira mi lodi npọ̀ si i.

20. Awọn ti o si nfi buburu san rere li ọta mi; nitori emi ntọpa ohun ti iṣe rere.

21. Oluwa, máṣe kọ̀ mi silẹ; Ọlọrun mi, máṣe jina si mi.

22. Yara lati ran mi lọwọ, Oluwa igbala mi.

O. Daf 38