O. Daf 119:115-120 Yorùbá Bibeli (YCE)

115. Kuro lọdọ mi, ẹnyin oluṣe-buburu: emi o si pa ofin Ọlọrun mi mọ́.

116. Gbé mi soke gẹgẹ bi ọ̀rọ rẹ, ki emi ki o le yè: ki o má si jẹ ki oju ireti mi ki o tì mi.

117. Gbé mi soke, emi o si wà li ailewu: emi o si juba ìlana rẹ nigbagbogbo.

118. Iwọ ti tẹ̀ gbogbo awọn ti o ṣina kuro ninu ilana rẹ mọlẹ: nitori pe ẹ̀tan ni ironu wọn.

119. Iwọ ṣá gbogbo awọn enia buburu aiye tì bi ìdarọ́: nitorina emi fẹ ẹri rẹ.

120. Ara mi warìri nitori ìbẹru rẹ; emi si bẹ̀ru idajọ rẹ.

O. Daf 119