O. Daf 109:1-11 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. MÁṢE pa ẹnu rẹ mọ́, Ọlọrun iyìn mi;

2. Nitori ti ẹnu awọn enia buburu, ati ẹnu awọn ẹlẹtan yà silẹ si mi: nwọn ti fi ahọn eke sọ̀rọ si mi.

3. Nwọn si fi ọ̀rọ irira yi mi ka kiri; nwọn si mba mi ja li ainidi.

4. Nipo ifẹ mi nwọn nṣe ọta mi: ṣugbọn emi ngba adura.

5. Nwọn si fi ibi san ire fun mi, ati irira fun ifẹ mi.

6. Yan enia buburu tì i: jẹ ki Olufisùn ki o duro li ọwọ ọtún rẹ̀.

7. Nigbati a o ṣe idajọ rẹ̀, ki a da a lẹbi: ki adura rẹ̀ ki o di ẹ̀ṣẹ;

8. Ki ọjọ rẹ̀ ki o kuru; ki ẹlomiran ki o rọpo iṣẹ rẹ̀.

9. Ki awọn ọmọ rẹ̀ ki o di alainibaba, ki aya rẹ̀ ki o di opó.

10. Jẹ ki awọn ọmọ rẹ̀ ki o di alarinkiri, ti nṣagbe: ki nwọn ki o ma tọrọ onjẹ jina si ibi ahoro wọn.

11. Jẹ ki alọnilọwọ-gbà ki o mu ohun gbogbo ti o ni; ki alejo ki o kó èrè iṣẹ́ rẹ̀ lọ.

O. Daf 109