Neh 11:4-10 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Ati ninu awọn ọmọ Juda ngbe Jerusalemu, ati ninu awọn ọmọ Benjamini. Ninu awọn ọmọ Juda, Ataiah ọmọ Ussiah, ọmọ Sekariah, ọmọ Amariah, ọmọ Ṣefatiah, ọmọ Mahalaleeli, ninu awọn ọmọ Peresi;

5. Ati Maaseiah ọmọ Baruku, ọmọ Kol-hose, ọmọ Hasaiah, ọmọ Adaiah, ọmọ Joiaribu, ọmọ Sekariah, ọmọ Ṣiloni.

6. Gbogbo ọmọ Peresi ti ngbe Jerusalemu jẹ adọrinlenirinwo o di meji, alagbara ọkunrin.

7. Wọnyi li awọn ọmọ Benjamini; Sallu ọmọ Meṣullamu ọmọ Joedi, ọmọ Pedaiah, ọmọ Kolaiah, ọmọ Maaseiah, ọmọ Itieli, ọmọ Jesaiah.

8. Ati lẹhin rẹ̀ Gabbai, Sallai, ọrindilẹgbẹrun o le mẹjọ.

9. Joeli ọmọ Sikri si ni alabojuto wọn; ati Juda ọmọ Senua ni igbakeji ni ilu.

10. Ninu awọn alufa: Jedaiah ọmọ Joiaribu, Jakini.

Neh 11