Luk 23:15-24 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Ati Herodu pẹlu: o sá rán a pada tọ̀ wa wá; si kiyesi i, ohun kan ti o yẹ si ikú a ko ṣe si i ti ọwọ́ rẹ̀ wá.

16. Njẹ emi ó nà a, emi ó si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

17. Ṣugbọn kò le ṣe aidá ọkan silẹ fun wọn nigba ajọ irekọja.

18. Nwọn si kigbe soke lọwọ kanna, wipe, Mu ọkunrin yi kuro, ki o si dá Barabba silẹ fun wa:

19. Ẹniti a sọ sinu tubu nitori ọ̀tẹ kan ti a ṣe ni ilu, ati nitori ipania.

20. Pilatu si tun ba wọn sọrọ, nitori o fẹ da Jesu silẹ.

21. Ṣugbọn nwọn kigbe, wipe, Kàn a mọ agbelebu, kàn a mọ agbelebu.

22. O si wi fun wọn li ẹrinkẹta pe, Ẽṣe, buburu kili ọkunrin yi ṣe? emi ko ri ọ̀ran ikú lara rẹ̀: nitorina emi o nà a, emi a si jọwọ rẹ̀ lọwọ lọ.

23. Nwọn tilẹ̀ kirimọ́ igbe nla, nwọn nfẹ ki a kàn a mọ agbelebu. Ohùn ti wọn ati ti awọn olori alufa bori tirẹ̀.

24. Pilatu si fi aṣẹ si i pe, ki o ri bi nwọn ti nfẹ.

Luk 23