Luk 1:46-53 Yorùbá Bibeli (YCE)

46. Maria si dahùn, o ni, Ọkàn mi yìn Oluwa logo,

47. Ẹmí mi si yọ̀ si Ọlọrun Olugbala mi.

48. Nitoriti o ṣijuwò ìwa irẹlẹ ọmọbinrin ọdọ rẹ̀: sá wò o, lati isisiyi lọ gbogbo iran enia ni yio ma pè mi li alabukunfun.

49. Nitori ẹniti o li agbara ti ṣe ohun ti o tobi fun mi; mimọ́ si li orukọ rẹ̀.

50. Anu rẹ̀ si mbẹ fun awọn ti o bẹ̀ru rẹ̀ lati irandiran.

51. O ti fi agbara hàn li apa rẹ̀; o ti tú awọn onirera ká ni ironu ọkàn wọn.

52. O ti mu awọn alagbara kuro lori itẹ́ wọn, o si gbé awọn talakà leke.

53. O ti fi ohun ti o dara kún awọn ti ebi npa; o si rán awọn ọlọrọ̀ pada lọwọ ofo.

Luk 1