Joh 14:13-20 Yorùbá Bibeli (YCE)

13. Ohunkohun ti ẹnyin ba si bère li orukọ mi, on na li emi ó ṣe, ki a le yìn Baba logo ninu Ọmọ.

14. Bi ẹnyin ba bère ohunkohun li orukọ mi, emi ó ṣe e.

15. Bi ẹnyin ba fẹran mi, ẹ ó pa ofin mi mọ́.

16. Emi ó si bère lọwọ Baba, on ó si fun nyin li Olutunu miran, ki o le mã ba nyin gbé titi lailai,

17. Ani Ẹmí otitọ nì; ẹniti araiye kò le gbà, nitoriti kò ri i, bẹ̃ni kò si mọ̀ ọ: ṣugbọn ẹnyin mọ̀ ọ; nitoriti o mba nyin gbe, yio si wà ninu nyin.

18. Emi kì o fi nyin silẹ li alaini baba: emi ó tọ̀ nyin wá.

19. Nigba diẹ si i, aiye ki ó si ri mi mọ́; ṣugbọn ẹnyin ó ri mi: nitoriti emi wà lãye, ẹnyin ó wà lãye pẹlu.

20. Li ọjọ na li ẹnyin o mọ̀ pe, emi wà ninu Baba mi, ati ẹnyin ninu mi, ati emi ninu nyin.

Joh 14