Jer 39:15-18 Yorùbá Bibeli (YCE)

15. Ọrọ Oluwa si tọ̀ Jeremiah wá, nigbati a se e mọ ninu àgbala ile-túbu, wipe,

16. Lọ, ki o si sọ fun Ebedmeleki, ara Etiopia, wipe: Bayi li Oluwa awọn ọmọ-ogun, Ọlọrun Israeli wi pe, wò o, emi o mu ọ̀rọ mi wá sori ilu yi fun ibi, kì isi ṣe fun rere; nwọn o si ṣẹ niwaju rẹ li ọjọ na.

17. Ṣugbọn emi o gbà ọ li ọjọ na, li Oluwa wi: a kì o si fi ọ le ọwọ awọn enia na ti iwọ bẹ̀ru.

18. Nitori emi o gbà ọ là nitõtọ, iwọ kì o si ti ipa idà ṣubu, ṣugbọn ẹ̀mi rẹ yio jẹ bi ikogun fun ọ: nitoripe iwọ ti gbẹkẹ rẹ le mi, li Oluwa wi.

Jer 39