Isa 21:11-14 Yorùbá Bibeli (YCE)

11. Ọ̀rọ-ìmọ niti Duma. O ké si mi lati Seiri wá, Oluṣọ́, oru ti ri? Oluṣọ́ oru ti ri?

12. Oluṣọ́ wipe, ilẹ nmọ́ bọ̀, alẹ si nlẹ pẹlu: bi ẹnyin o ba bere, ẹ bere: ẹ pada, ẹ wá.

13. Ọ̀rọ-ìmọ niti Arabia. Ninu igbó Arabia li ẹnyin o wọ̀, ẹnyin ẹgbẹ́-erò Dedanimu.

14. Awọn olugbé ilẹ Tema bù omi wá fun ẹniti ongbẹ ngbẹ, onjẹ wọn ni nwọn fi ṣaju ẹniti nsalọ.

Isa 21