2. Kro 28:4-6 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. O si rubọ, o si sun turari ni ibi giga wọnni, ati lori òke kekere, ati labẹ gbogbo igi tutu.

5. Nitorina Oluwa Ọlọrun rẹ̀ fi i le ọba Siria lọwọ; nwọn si kọlù u, nwọn si kó ọ̀pọlọpọ ni igbekun lọ ninu wọn, nwọn si mu wọn wá si Damasku. A si fi i le ọba Israeli lọwọ pẹlu, ti o pa a ni ipakupa.

6. Nitoriti Peka, ọmọ Remaliah, pa ọkẹ mẹfa enia ni Juda ni ijọ kan, gbogbo awọn ọmọ-ogun: nitoriti nwọn ti kọ̀ Oluwa, Ọlọrun awọn baba wọn silẹ.

2. Kro 28