2. Kro 26:1-10 Yorùbá Bibeli (YCE)

1. NIGBANA ni gbogbo enia Juda mu Ussiah ti iṣe ẹni ọdun mẹrindilogun, nwọn si fi i jọba ni ipò baba rẹ̀, Amasiah.

2. On kọ́ Elotu, o si mu u pada fun Juda; lẹhin ti ọba sùn pẹlu awọn baba rẹ̀.

3. Ẹni ọdun mẹrindilogun ni Ussiah, nigbati o bẹ̀rẹ si ijọba, o si jọba ọdun mejilelãdọta ni Jerusalemu. Orukọ iya rẹ̀ si ni Jekoliah ti Jerusalemu.

4. O si ṣe eyiti o tọ́ li oju Oluwa, gẹgẹ bi gbogbo eyiti baba rẹ̀, Amasiah, ti ṣe.

5. O si wá Ọlọrun li ọjọ Sekariah, ẹniti o li oye ninu iran Ọlọrun: niwọn ọjọ ti o wá Oluwa, Ọlọrun si mu u ṣe rere.

6. O si jade lọ, o si ba awọn ara Filistia jagun, o si wó odi Gati ati odi Jabne ati odi Aṣdodu, o si kọ́ ilu wọnni ni Aṣdodu, ati lãrin awọn ara Filistia.

7. Ọlọrun si ràn a lọwọ si awọn ara Filistia, ati si awọn ara Arabia, ti ngbe ni Gur-Baali, ati awọn ara Mehuni.

8. Awọn ara Ammoni ta Ussiah li ọrẹ: orukọ rẹ̀ si tàn lọ kakiri titi de atiwọ Egipti; nitoriti o mu ara rẹ̀ le gidigidi.

9. Ussiah si kọ́ ile iṣọ ni Jerusalemu, nibi ẹnu-bode Igun, ati nibi ẹnu-bode Afonifoji, ati nibi iṣẹpo-odi, o si mu wọn le.

10. O kọ́ ile iṣọ li aginju pẹlu, o si wà kanga pupọ: nitoriti o li ẹran-ọsin pipọ, ati ni ilẹ isalẹ, ati ni pẹ̀tẹlẹ: o ni àgbẹ ati awọn olutọju àjara lori òke nla, ati lori Karmeli: nitoriti o fẹran àgbẹ-ṣiṣe.

2. Kro 26