1. Kor 15:31-36 Yorùbá Bibeli (YCE)

31. Mo sọ nipa ayọ̀ ti mo ni lori nyin ninu Kristi Jesu Oluwa wa pe, emi nkú lojojumọ́.

32. Ki a wi bi enia, bi mo ba ẹranko jà ni Efesu, anfãni kili o jẹ́ fun mi? bi o ba ṣe pe awọn okú kò jinde, ẹ jẹ ki a mã jẹ, ẹ jẹ ki a mã mu; ọla li awa o sá kú.

33. Ki a má tàn nyin jẹ: ẹgbẹ́ buburu bà ìwa rere jẹ.

34. Ẹ jí iji ododo, ki ẹ má si dẹṣẹ̀; nitori awọn ẹlomiran kò ni ìmọ Ọlọrun: mo sọ eyi ki oju ki o le ti nyin.

35. Ṣugbọn ẹnikan yio wipe, Bawo li a o ha ji awọn okú dide? iru ara wo ni nwọn o pada si?

36. Iwọ alaimoye, ohun ti iwọ fọnrugbin ki iyè bikoṣepe o ba kú:

1. Kor 15