Hos 13:5-12 Yorùbá Bibeli (YCE)

5. Emi ti mọ̀ ọ li aginjù, ni ilẹ ti o pongbẹ.

6. Gẹgẹ bi a ti bọ́ wọn, bẹ̃ni nwọn yó; nwọn yó, nwọn si gbe ọkàn wọn ga; nitorina ni nwọn ṣe gbagbe mi.

7. Nitorina li emi o ṣe dabi kiniun si wọn; emi o si ma ṣọ wọn bi ẹkùn li ẹ̀ba ọ̀na.

8. Emi o pade wọn bi beari ti a gbà li ọ̀mọ, emi o si fà àwọn ọkàn wọn ya, nibẹ̀ ni emi o si jẹ wọn run bi kiniun, ẹranko igbẹ ni yio fà wọn ya.

9. Israeli, iwọ ti pa ara rẹ run, niti pe iwọ wà lodi si emi, irànlọwọ rẹ.

10. Nibo li ọba rẹ gbe wà nisisiyi ninu gbogbo ilu rẹ, ti o le gbà ọ? ati awọn onidajọ rẹ, niti awọn ti iwọ wipe; Fun mi li ọba ati awọn ọmọ-alade.

11. Emi fun ọ li ọba ni ibinu mi, mo si mu u kuro ni irúnu mi.

12. A dì aiṣedẽde Efraimu; ẹ̀ṣẹ rẹ̀ pamọ.

Hos 13