Heb 10:12-21 Yorùbá Bibeli (YCE)

12. Ṣugbọn on, lẹhin igbati o ti ru ẹbọ kan fun ẹ̀ṣẹ titi lai, o joko li ọwọ́ ọtún Ọlọrun;

13. Lati igbà na lọ, ó nreti titi a o fi fi awọn ọtá rẹ̀ ṣe apoti itisẹ rẹ̀.

14. Nitori nipa ẹbọ kan o ti mu awọn ti a sọ di mimọ́ pé titi lai.

15. Ẹmí Mimọ́ si njẹri fun wa pẹlu: nitori lẹhin ti o ti wipe,

16. Eyi ni majẹmu ti emi ó ba wọn dá lẹhin ọjọ wọnni, li Oluwa wi, emi o fi ofin mi si wọn li ọkàn, inu wọn pẹlu li emi o si kọ wọn si;

17. Ẹ̀ṣẹ wọn ati aiṣedede wọn li emi kì yio si ranti mọ́.

18. Ṣugbọn nibiti imukuro iwọnyi ba gbé wà, irubọ fun ẹ̀ṣẹ kò si mọ́.

19. Ará, njẹ bi a ti ni igboiya lati wọ̀ inu ibi mimọ́ nipasẹ ẹ̀jẹ Jesu,

20. Nipa ọ̀na titun ati ãye, ti o yà si mimọ́ fun wa, ati lati kọja aṣọ ikele nì, eyini ni, ara rẹ̀;

21. Ati bi a ti ni alufa giga lori ile Ọlọrun;

Heb 10