Esr 8:30-36 Yorùbá Bibeli (YCE)

30. Bẹ̃ni awọn alufa ati awọn ọmọ Lefi mu fàdaka ati wura ti a wọ̀n pẹlu ohun-èlo wọnni lati ko wọn wá si Jerusalemu, sinu ile Ọlọrun wa.

31. Nigbana ni awa lọ kuro ni odò Ahafa, li ọjọ ekejila oṣu ikini, lati lọ si Jerusalemu: ọwọ Ọlọrun wa si wà lara wa, o si gba wa lọwọ awọn ọta, ati lọwọ iru awọn ti o ba ni ibuba li ọ̀na.

32. Awa si de Jerusalemu, awa si simi nibẹ li ọjọ mẹta.

33. Li ọjọ ẹkẹrin li a wọ̀n fàdaka ati wura ati ohun-èlo wọnni ninu ile Ọlọrun wa si ọwọ Meremoti ọmọ Uriah, alufa, ati pẹlu rẹ̀ ni Eleasari ọmọ Finehasi; ati pẹlu wọn ni Josabadi ọmọ Jeṣua, ati Noadia, ọmọ Binnui, awọn ọmọ Lefi;

34. Nipa iye, ati nipa ìwọn ni gbogbo wọn: a si kọ gbogbo ìwọn na sinu iwe ni igbana.

35. Ọmọ awọn ti a ti ko lọ, awọn ti o ti inu igbekùn pada bọ̀, ru ẹbọ sisun si Ọlọrun Israeli, ẹgbọrọ malu mejila, àgbo mẹrindilọgọrun, ọdọ-agutan mẹtadilọgọrin, ati obukọ mejila fun ẹbọ ẹ̀ṣẹ: gbogbo eyi jẹ ẹbọ sisun si Oluwa.

36. Nwọn si fi aṣẹ ọba fun awọn ijoye ọba, ati fun awọn balẹ ni ihahin odò: nwọn si ràn awọn enia na lọwọ, ati ile Ọlọrun.

Esr 8