Esek 6:6-10 Yorùbá Bibeli (YCE)

6. Ilu-nla li a o parun ninu gbogbo ibugbe nyin, ibi giga yio si di ahoro: ki a le run pẹpẹ nyin, ki a si sọ ọ di ahoro, ki a si le fọ́ oriṣa nyin, ki o si tan, ki a si le ké ere nyin lu ilẹ, ki iṣẹ́ nyin si le parẹ.

7. Okú yio si ṣubu li ãrin nyin, ẹnyin o si mọ̀ pe, Emi li Oluwa.

8. Ṣugbọn emi o fi iyokú silẹ, ki ẹnyin le ni diẹ ti yio bọ́ lọwọ idà lãrin awọn orilẹ-ède, nigbati a o tú nyin ka gbogbo ilẹ.

9. Awọn ti o bọ́ ninu nyin yio si ranti mi, lãrin awọn orilẹ-ède nibiti nwọn o gbe dì wọn ni igbekun lọ, nitoriti mo ti fọ́ ọkàn agbere wọn ti o ti lọ kuro lọdọ mi, ati pẹlu oju wọn, ti nṣagbere lọ sọdọ oriṣa wọn: nwọn o si sú ara wọn nitori ìwa ibi ti nwọn ti hù ninu gbogbo irira wọn.

10. Nwọn o si mọ̀ pe emi li Oluwa, emi kò wi lasan pe, emi o ṣe ibi yi si wọn.

Esek 6