Esek 32:12-15 Yorùbá Bibeli (YCE)

12. Emi o mu ki ọ̀pọlọpọ enia rẹ ṣubu nipa idà awọn alagbara, ẹlẹ́rù awọn orilẹ-ẹ̀de ni gbogbo wọn; nwọn o si bà afẹ́ Egipti jẹ́, ati gbogbo ọ̀pọlọpọ enia rẹ̀ ni nwọn o parun.

13. Emi o si pa gbogbo awọn ẹranko inu rẹ̀ run kuro lẹba awọn omi nla, bẹ̃ni ẹsẹ enia kì yio rú wọn mọ́ lailai, tabi pátakò awọn ẹranko kì yio rú wọn.

14. Nigbana li emi o mu ki omi wọn ki o rẹlẹ, emi o si mu ki odò wọn ki o ṣàn bi oróro, li Oluwa Ọlọrun wi.

15. Nigbati emi o mu ki ilẹ Egipti di ahoro ti ilẹ na yio si di alaini ohun ti o kún inu rẹ̀ ri, nigbati emi o kọlù gbogbo awọn ti ngbe inu rẹ̀, nigbana ni nwọn o mọ̀ pe emi li Oluwa.

Esek 32