Esek 24:4-9 Yorùbá Bibeli (YCE)

4. Kó aján na jọ sinu rẹ̀, olukuluku aján ti o tobi, itan, ati apá, fi egungun ti o jọju kún inu rẹ̀.

5. Mu ninu agbo-ẹran ti o jọju, ko awọn egungun sabẹ rẹ̀, si jẹ ki o hó dãdã, si jẹ ki nwọn bọ̀ egungun rẹ̀ ninu rẹ̀.

6. Nitorina bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Egbé ni fun ilu ẹlẹjẹ na, fun ìkoko ti ifõfo rẹ̀ wà ninu rẹ̀, ti ifõfo rẹ̀ kò dá loju rẹ̀: mu u jade li aján li aján; máṣe dìbo nitori rẹ̀.

7. Nitori ẹjẹ rẹ̀ wà lãrin rẹ̀, o gbé e kà ori apata kan, kò tú u dà sori ilẹ, lati fi erupẹ bò o.

8. Ki o ba lè jẹ ki irúnu ki o de, lati gbẹsan; mo ti gbe ẹjẹ rẹ̀ kà ori apata kan, ki a má ba le bò o.

9. Nitorina, bayi li Oluwa Ọlọrun wi; Egbe ni fun ilu ẹlẹjẹ na! Emi o tilẹ jẹ ki òkiti iná na tobi.

Esek 24