Deu 28:31-37 Yorùbá Bibeli (YCE)

31. A o si pa akọmalu rẹ li oju rẹ, iwọ ki yio si jẹ ninu rẹ̀: kẹtẹkẹtẹ rẹ li a o si fi agbara mú lọ kuro li oju rẹ, a ki yio si mú u pada fun ọ wá: a o fi agutan rẹ fun awọn ọtá rẹ, iwọ ki yio si lí ẹniti yio gbà ọ.

32. Awọn ọmọ rẹ ọkunrin, ati awọn ọmọ rẹ obinrin, li a o fi fun enia miran, oju rẹ yio ma wò, yio si su ọ lati ma wò ọ̀na wọn li ọjọ́ gbogbo: ki yio si sí agbara kan li ọwọ́ rẹ.

33. Eso ilẹ rẹ, ati gbogbo iṣẹ-lãlã rẹ, ni orilẹ-ède miran ti iwọ kò mọ̀ yio jẹ; iwọ o si jẹ́ kìki ẹni inilara ati ẹni itẹmọlẹ nigbagbogbo:

34. Bẹ̃ni iwọ o si di aṣiwere nitori iran oju rẹ, ti iwọ o ri.

35. OLUWA yio si fi õwo buburu lù ọ li ẽkún, ati li ẹsẹ̀, ti a ki o le wòsan, lati atẹlẹsẹ̀ rẹ dé atari rẹ.

36. OLUWA o mú iwọ, ati ọba rẹ ti iwọ o fi jẹ́ lori rẹ, lọ si orilẹ-ède ti iwọ, ati awọn baba rẹ kò mọ̀ rí; iwọ o si ma bọ oriṣa nibẹ̀, igi ati okuta.

37. Iwọ o si di ẹni iyanu, ati ẹni owe, ati ẹni ifisọrọsọ, ninu gbogbo orilẹ-ède, nibiti OLUWA yio gbé darí rẹ si.

Deu 28