Samuẹli Kinni 30:25-31 BIBELI MIMỌ (BM)

25. Láti ọjọ́ náà ni ó ti sọ ọ́ di òfin ati ìlànà ní Israẹli, títí di òní olónìí.

26. Nígbà tí Dafidi pada dé Sikilagi, ó fi ẹ̀bùn ranṣẹ sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀ tí wọ́n jẹ́ olórí Juda; ó mú ninu ìkógun náà, ó ní, “Ẹ̀bùn yín nìyí lára ìkógun tí a kó láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá OLUWA.”

27. Ó fi ranṣẹ sí àwọn tí wọ́n wà ní Bẹtẹli, ati àwọn tí wọ́n wà ní Ramoti ti Nẹgẹbu, ati Jatiri;

28. ati àwọn tí wọ́n wà ní Aroeri, Sifimoti, ati ní Eṣitemoa;

29. ní Rakali, ní àwọn ìlú Jerameeli, àwọn ìlú Keni,

30. ní Homa, Boraṣani, ati ní Ataki,

31. ní Heburoni ati ní gbogbo ìlú tí Dafidi ati àwọn ọmọlẹ́yìn rẹ̀ ti rìn kiri.

Samuẹli Kinni 30