Samuẹli Kinni 2:7-10 BIBELI MIMỌ (BM)

7. OLUWA ni ó lè sọni di aláìní,òun náà ni ó sì lè sọ eniyan di ọlọ́rọ̀.Òun ni ó ń gbéni ga,òun náà ni ó sì ń rẹ eniyan sílẹ̀.

8. OLUWA ń gbé talaka dìde láti ipò ìrẹ̀lẹ̀;ó ń gbé aláìní dìde láti inú òṣì rẹ̀,láti mú wọn jókòó pẹlu àwọn ọmọ ọba,kí wọ́n sì wà ní ipò ọlá.Nítorí pé òun ni ó ni àwọn ìpìlẹ̀ ayé,òun ni ó sì gbé ayé kalẹ̀ lórí wọn.

9. “Yóo pa àwọn olóòótọ́ tí wọ́n jẹ́ tirẹ̀ mọ́,ṣugbọn yóo mú kí àwọn eniyan burúkú parẹ́ ninu òkùnkùn;nítorí pé, kì í ṣe nípa agbára eniyan, ni ẹnikẹ́ni lè fi ṣẹgun.

10. Àwọn ọ̀tá OLUWA yóo parun;OLUWA yóo sán ààrá pa wọ́n láti ojú ọ̀run wá.OLUWA yóo ṣe ìdájọ́ gbogbo ayé,yóo fún ọba rẹ̀ lágbára,yóo sì fún ẹni tí ó yàn ní ìṣẹ́gun.”

Samuẹli Kinni 2