1. Ọ̀rọ̀ ìkẹyìn Dafidi nìyí; àní, ọ̀rọ̀ ìjìnlẹ̀ Dafidi, ọmọ Jese, tí a gbé ga ní Israẹli, ẹni àmì òróró Ọlọrun Jakọbu, olórin dídùn ní Israẹli:
2. “Ẹ̀mí OLUWA ń gba ẹnu mi sọ̀rọ̀,ọ̀rọ̀ rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
3. Ọlọrun Israẹli ti sọ̀rọ̀,Àpáta Israẹli ti wí fún mi pé,‘Ẹni yòówù tí ó bá fi òtítọ́ jọba,tí ó ṣe àkóso pẹlu ìbẹ̀rù Ọlọrun,
4. a máa tàn sí wọn bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀,bí oòrùn tí ó ń ràn ní òwúrọ̀ kutukutu,ní ọjọ́ tí kò sí ìkùukùu;ó dàbí òjò tí ń mú kí koríko hù jáde láti inú ilẹ̀.’