Orin Solomoni 6:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Níbo ni olùfẹ́ rẹ lọ,ìwọ, arẹwà jùlọ láàrin àwọn obinrin?Níbo ni olùfẹ́ rẹ yà sí,kí á lè bá ọ wá a?

2. Olùfẹ́ mi ti lọ sinu ọgbà rẹ̀,níbi ebè igi turari,ó da ẹran rẹ̀ lọ sinu ọgbà,ó lọ já òdòdó lílì.

3. Olùfẹ́ mi ló ni mí,èmi ni mo sì ni olùfẹ́ mi.Láàrin òdòdó lílì,ni ó ti ń da ẹran rẹ̀.

4. Olùfẹ́ mi, o dára bíi Tirisa.O lẹ́wà bíi Jerusalẹmu,O níyì bíi ọ̀wọ́ àwọn ọmọ ogun tí ń gbé ọ̀págun.

5. Yíjú kúrò lọ́dọ̀ mi,nítorí wọn kò jẹ́ kí n gbádùn.Irun orí rẹ dàbí ọ̀wọ́ ewúrẹ́ ninu agbo,tí ń sọ̀kalẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Gileadi.

6. Eyín rẹ dàbí ọ̀wọ́ aguntan,tí wọn ṣẹ̀ṣẹ̀ wẹ̀ tán,gbogbo wọn gún régé,kò sì sí ọ̀kan tí ó yọ ninu wọn,

7. Ẹ̀rẹ̀kẹ́ rẹ dàbí ìlàjì èso pomegiranate lábẹ́ ìbòjú rẹ.

Orin Solomoni 6