Orin Dafidi 96:11-13 BIBELI MIMỌ (BM)

11. Jẹ́ kí inú ọ̀run ó dùn, sì jẹ́ kí ayé ó yọ̀;kí òkun ó hó, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀.

12. Jẹ́ kí pápá oko ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀ yọ̀.Nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóo fi ayọ̀ kọrin,

13. níwájú OLUWA, nítorí pé ó ń bọ̀;ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé.Yóo fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé;yóo sì fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ àwọn eniyan.

Orin Dafidi 96