Orin Dafidi 94:9-13 BIBELI MIMỌ (BM)

9. Ṣé ẹni tí ó dá etí, ni kò ní gbọ́ràn?Àbí ẹni tí ó dá ojú, ni kò ní ríran?

10. Ṣé ẹni tí ń jẹ àwọn orílẹ̀-èdè níyà,ni kò ní jẹ yín níyà?Àbí ẹni tí ń fún eniyan ní ìmọ̀, ni kò ní ní ìmọ̀?

11. OLUWA mọ èrò ọkàn ọmọ eniyan,ó mọ̀ pé afẹ́fẹ́ lásán ni.

12. Ayọ̀ ń bẹ fún ẹni tí o bá báwí, OLUWA,tí o sì kọ́ ní òfin rẹ,

13. kí ó lè sinmi lọ́wọ́ ọjọ́ ìṣòro,títí tí a ó fi gbẹ́ kòtò fún eniyan burúkú.

Orin Dafidi 94