Orin Dafidi 94:16-22 BIBELI MIMỌ (BM)

16. Ta ni yóo bá mi dìde sí àwọn eniyan burúkú?Ta ni yóo bá mi dìde sí àwọn aṣebi?

17. Bí kì í bá ṣe pé OLUWA ràn mí lọ́wọ́,ǹ bá ti dákẹ́ jẹ́ẹ́ ní isà òkú.

18. Nígbà tí mo rò pé, “Ẹsẹ̀ mi ti yọ̀,”OLUWA, ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ ni ó gbé mi ró.

19. Nígbà tí àìbàlẹ̀ ọkàn mi pọ̀ pupọ,ìwọ ni o tù mí ninu, tí o dá mi lọ́kàn le.

20. Ǹjẹ́ o lè ní àjọṣe pẹlu àwọn ìkà aláṣẹ,àwọn tí ń fi òfin gbé ìwà ìkà ró?

21. Wọ́n para pọ̀ láti gba ẹ̀mí olódodo;wọ́n sì dá ẹjọ́ ikú fún aláìṣẹ̀.

22. Ṣugbọn OLUWA ti di ibi ìsádi mi,Ọlọrun mi sì ti di àpáta ààbò mi.

Orin Dafidi 94