Orin Dafidi 94:1-6 BIBELI MIMỌ (BM)

1. OLUWA, ìwọ Ọlọrun ẹ̀san,ìwọ Ọlọrun ẹ̀san, fi agbára rẹ hàn!

2. Dìde, ìwọ onídàájọ́ ayé;san ẹ̀san èrè iṣẹ́ àwọn agbéraga fún wọn!

3. OLUWA, yóo ti pẹ́ tó?Àní, yóo ti pẹ́ tó tí àwọn eniyan burúkú yóo máa ṣe jàgínní?

4. Wọ́n ń fi ìgbéraga sọ̀rọ̀ jàbùjàbù,gbogbo àwọn aṣebi ní ń fọ́nnu.

5. Wọ́n ń rún àwọn eniyan rẹ mọ́lẹ̀, OLUWA,wọ́n ń pọ́n àwọn eniyan rẹ lójú.

6. Wọ́n ń pa àwọn opó ati àwọn àlejò,wọ́n sì ń pa àwọn aláìníbaba;

Orin Dafidi 94