Orin Dafidi 88:6-10 BIBELI MIMỌ (BM)

6. O ti fi mí sinu isà òkú tí ó jìn pupọ,ninu òkùnkùn, àní ninu ọ̀gbun.

7. Ọwọ́ ibinu rẹ wúwo lára mi,ìgbì ìrúnú rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.

8. O ti mú kí àwọn ọ̀rẹ́ kòríkòsùn mi fi mí sílẹ̀;mo sì ti di ẹni ìríra lọ́dọ̀ wọn:mo wà ninu àhámọ́, n kò sì lè jáde;

9. ojú mi ti di bàìbàì nítorí ìbànújẹ́.Lojoojumọ ni mò ń ké pè ọ́, OLUWA;tí mò ń tẹ́wọ́ adura sí ọ.

10. Ṣé òkú ni o óo ṣe iṣẹ́ ìyanu hàn?Ṣé àwọn òkú lè dìde kí wọ́n máa yìn ọ́?

Orin Dafidi 88