2. Wò ó! Àwọn ọ̀tá rẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọ;àwọn tí ó kórìíra rẹ sì ń yájú sí ọ.
3. Wọ́n pète àrékérekè sí àwọn eniyan rẹ;wọ́n sì gbìmọ̀ pọ̀ sí àwọn tí ó sá di ọ́.
4. Wọ́n ní, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á pa orílẹ̀-èdè wọn run;kí á má ranti orúkọ Israẹli mọ́!”
5. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ pète pèrò;wọ́n dá majẹmu láti dojú kọ ọ́.
6. Àwọn ará Edomu, ati àwọn ọmọ Iṣimaeli,àwọn ará Moabu, ati àwọn ọmọ Hagiri,