Orin Dafidi 78:38-45 BIBELI MIMỌ (BM)

38. Sibẹ, nítorí pé aláàánú ni, ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ wọn jì wọ́n,kò sì pa wọ́n run;ní ọ̀pọ̀ ìgbà ni ó dáwọ́ ibinu rẹ̀ dúró,tí kò sì fi gbogbo ara bínú sí wọn.

39. Ó ranti pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,afẹ́fẹ́ lásán tí ń fẹ́ kọjá lọ, tí kò sì ní pada mọ́.

40. Ìgbà mélòó ni wọ́n ṣọ̀tẹ̀ sí i ninu ijù,tí wọ́n sì bà á lọ́kàn jẹ́ ninu aṣálẹ̀!

41. Wọ́n dán an wò léraléra,wọ́n sì mú Ẹni Mímọ́ Israẹli bínú.

42. Wọn kò ranti agbára rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ranti ọjọ́ tí ó rà wọ́n pada lọ́wọ́ ọ̀tá;

43. nígbà tí ó ṣe iṣẹ́ abàmì ní ilẹ̀ Ijipti,tí ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní oko Soani.

44. Ó sọ omi odò wọn di ẹ̀jẹ̀,tí wọn kò fi lè mu omi wọn.

45. Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin sí wọn tí ó jẹ wọ́n,ati ọ̀pọ̀lọ́ tí ó pa wọ́n run.

Orin Dafidi 78