Orin Dafidi 69:5-14 BIBELI MIMỌ (BM)

5. Ọlọrun, o mọ ìwà òmùgọ̀ mi,àwọn àṣìṣe mi kò sì fara pamọ́ fún ọ.

6. Má tìtorí tèmi dójúti àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ,OLUWA Ọlọrun àwọn ọmọ ogun,má sì tìtorí mi sọ àwọn tí ń wá ọ di ẹni àbùkù,Ọlọrun Israẹli.

7. Nítorí tìrẹ ni mo ṣe di ẹni ẹ̀gàn,tí ìtìjú sì bò mí.

8. Mo ti di àlejò lọ́dọ̀ àwọn arakunrin mi,mo sì di àjèjì lọ́dọ̀ àwọn ọmọ ìyá mi.

9. Nítorí pé ìtara ilé rẹ ni ó jẹ mí lógún,ìwọ̀sí àwọn tí ó ń pẹ̀gàn rẹ sì bò mí mọ́lẹ̀.

10. Nígbà tí mo fi omijé gbààwẹ̀,ó di ẹ̀gàn fún mi.

11. Nígbà tí mò ń wọ aṣọ ọ̀fọ̀,mo di ẹni àmúpòwe.

12. Èmi ni àwọn tí ń jókòó lẹ́nu ibodèfi ń ṣe ọ̀rọ̀ sọ;àwọn ọ̀mùtí sì ń fi mí ṣe orin kọ.

13. Ṣugbọn ní tèmi, OLUWA, ìwọ ni mò ń gbadura síní àkókò tí ó bá yẹ, Ọlọrun,ninu ọ̀pọ̀ ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀,ninu agbára ìgbàlà rẹ, Ọlọrun dá mi lóhùn.

14. Yọ mí ninu irà yìí, má jẹ́ kí n rì,gbà mí kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá mi.

Orin Dafidi 69