Orin Dafidi 63:1-7 BIBELI MIMỌ (BM)

1. Ọlọrun, ìwọ ni Ọlọrun mi, mò ń wá ọ,ọkàn rẹ ń fà mí;bí ilẹ̀ tí ó ti ṣá, tí ó sì gbẹṣe máa ń kóǹgbẹ omi.

2. Mo ti ń wò ọ́ ninu ilé mímọ́ rẹ,mo ti rí agbára ati ògo rẹ.

3. Nítorí ìfẹ́ rẹ tí kì í yẹ̀ dára ju ìyè lọ,n óo máa yìn ọ́.

4. N óo máa yìn ọ́ títí ayé mi;n óo máa tẹ́wọ́ adura sí ọ.

5. Ẹ̀mí mi yóo ní ànító ati àníṣẹ́kù;n óo sì fi ayọ̀ kọ orin ìyìn sí ọ.

6. Nígbà tí mo bá ranti rẹ lórí ibùsùn mi,tí mo bá ń ṣe àṣàrò nípa rẹ ní gbogbo òru;

7. nítorí ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ mi,lábẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ ni mò ń fi ayọ̀ kọrin.

Orin Dafidi 63