Orin Dafidi 60:3-7 BIBELI MIMỌ (BM)

3. O ti jẹ́ kí àwọn eniyan rẹ ní ọpọlọpọ ìnira,o ti fún wa ní ọtí mu tóbẹ́ẹ̀ tí à ń ta gbọ̀n-ọ́n-gbọ̀n-ọ́n.

4. O ti ta àsíá ogun fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ,kí wọ́n baà lè rí ààbò lọ́wọ́ ọfà ọ̀tá.

5. Kí á lè gba àyànfẹ́ rẹ là,fi ọwọ́ agbára rẹ ṣẹgun fún wa,kí o sì dá wa lóhùn.

6. Ọlọrun ti sọ̀rọ̀ ninu ilé mímọ́ rẹ̀,ó ní, “Tayọ̀tayọ̀ ni n óo fi pín Ṣekemu,n óo sì pín àfonífojì Sukotu.

7. Tèmi ni Gileadi, tèmi sì ni Manase;Efuraimu ni àkẹtẹ̀ àṣíborí mi,Juda sì ni ọ̀pá àṣẹ mi.

Orin Dafidi 60