Orin Dafidi 55:2-9 BIBELI MIMỌ (BM)

2. Fetí sí mi, kí o sì dá mi lóhùn;ìṣòro ti borí mi.

3. Ìhàlẹ̀ ọ̀tá bà mí ninu jẹ́,nítorí ìnilára àwọn eniyan burúkú;wọ́n kó ìyọnu bá mi,wọ́n ń bínú mi, inú wọn sì dùn láti máa bá mi ṣọ̀tá.

4. Ọkàn mi wà ninu ìrora,ìpayà ikú ti dé bá mi.

5. Ẹ̀rù ati ìwárìrì dà bò mí,ìpayà sì bò mí mọ́lẹ̀.

6. Mo ní, “Èmi ìbá ní ìyẹ́ bí àdàbà!Ǹ bá fò lọ, ǹ bá lọ sinmi.

7. Áà! Ǹ bá lọ jìnnà réré,kí n lọ máa gbé inú ijù;

8. ǹ bá yára lọ wá ibi ààbòkúrò lọ́wọ́ afẹ́fẹ́ líle ati ìjì.”

9. Da èrò wọn rú, OLUWA,kí o sì dà wọ́n lédè rú;nítorí ìwà ipá ati asọ̀ pọ̀ ninu ìlú.

Orin Dafidi 55